Alaga ẹgbẹ oṣelu New Nigeria Peoples Party nipinlẹ Ọṣun, Dokita Tosin Ọdẹyẹmi, ti kọwe fi ẹgbẹ oṣelu naa silẹ bayii.
Ọdẹyẹmi, ẹni to ti n tukọ ẹgbẹ naa lati nnkan bii ọdun mẹfa sẹyin, la gbọ pe o kọwe fi ẹgbẹ silẹ lọjọ Kẹrindinlogun, oṣu Keje, ti a wa yii latari wahala to n mi ẹgbẹ naa logbologbo lorileede Naijiria bayii.
Ṣugbọn bi Ọdẹyẹmi ṣe fi ẹgbẹ silẹ la gbọ pe ọja tu fun ẹgbẹ naa, ṣe lawọn oloye atawọn ọmọ ẹgbẹ n fiwe silẹ, ti wọn lawọn o ṣe mọ.
Igbakeji adari awọn obinrin lorileede yii, Hon. Ṣọlape Ọlatunbọsun ati akọwe fun ẹkun Guusu Iwọ-Oorun, Hon. Ọlalekan Fabayọ, sọ pe awọn ko ṣe ẹgbẹ NNPP mọ lẹyin ti awọn ṣagbeyẹwo bi ọjọọwaju ẹgbẹ naa ṣe n lọ.
Bakan naa ni igbakeji akọwe ẹgbẹ l'Ọṣun, Adegbaju Celestinah, akọwe alamojuto, IfẹOluwa Akinfala, alaga ẹgbẹ ni ẹkun idibo Ifẹ/Ijeṣa, Prophet Peter O. Blessed ati igbakeji adari awọn obinrin nipinlẹ Ọṣun, Arabinrin Ọladoṣu, la gbọ pe awọn naa ti kọwe fi ẹgbẹ ọhun silẹ bayii.
A o maa fi ẹkunrẹrẹ nipa bo ṣe n lọ ninu ẹgbẹ naa to yin leti.

No comments:
Post a Comment